1 Crônicas 14

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Nísinsin yìí Hiramu àti ọba Tire rán oníṣẹ́ sí Dafidi, àti pẹ̀lú igi kedari pẹ̀lú àwọn ọ̀mọ̀lé àti gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ààfin fún un.
1 Ora, Hirão, rei de Tiro, enviou mensageiros até Davi, e madeira de cedro, com pedreiros e carpinteiros, para lhe edificar uma casa.
2 Dafidi sì mọ Israẹli àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Israẹli àti pé ìjọba rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwọn ènìyàn rẹ̀.
2 E Davi percebeu que o ­SENHOR lhe havia confirmado rei sobre Israel, porque o seu reino tinha sido muito exaltado, por causa do seu povo, Israel.
3 Ní Jerusalẹmu Dafidi mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di baba àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin.
3 E Davi tomou mais esposas em Jerusalém; e Davi gerou mais filhos e filhas.
4 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣammua, Ṣobabu, Natani, Solomoni,
4 Ora estes são os nomes dos seus filhos, os quais ele teve em Jerusalém: Samua, e Sobabe, Natã, e Salomão,
5 Ibhari, Eliṣua, Elifeleti,
5 e Ibar, e Elisua, e Elpelete,
6 Noga, Nefegi, Jafia,
6 e Nogá, e Nefegue, e Jafia,
7 Eliṣama, Beeliada, àti Elifeleti.
7 e Elisama, e Beeliada, e Elifelete.
8 Nígbà tí àwọn ará Filistini gbọ́ pé a ti fi àmì òróró yàn Dafidi ní ọba lórí gbogbo Israẹli, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dafidi gbọ́ nípa rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn.
8 E, quando os filisteus, ouviram que Davi fora ungido rei sobre todo o Israel, todos os filisteus subiram em busca de Davi. E Davi ouviu isto, e saiu contra eles.
9 Nísinsin yìí àwọn ará Filistini ti wá láti gbógun ti àfonífojì Refaimu;
9 E os filisteus também vieram e se espalharam no vale dos Refains.
10 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé, “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Filistini lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ́n lé mi lọ́wọ́?”
10 E Davi consultou a DEUS, dizendo: Subirei contra os filisteus, e nas minhas mãos entregarás? E o ­SENHOR disse a ele: Sobe, porque amanhã eu os entregarei na tua mão.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Perasimu, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dafidi lórí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Perasimu.
11 Assim, eles subiram até Baal-Perazim; e Davi os feriu ali. Então, Davi disse: Deus irrompeu sobre os meus inimigos por intermédio da minha mão, como o irromper de águas; porquanto chamaram o nome daquele lugar Baal-Perazim.
12 Àwọn ará Filistini sì ti fi àwọn òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀. Dafidi sì pa á láṣẹ láti jó wọn nínú iná.
12 E quando eles haviam deixado ali os seus deuses, Davi deu um mandamento, e eles foram queimados com fogo.
13 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn ará Filistini gbógun wọ́n sì fọ́nká àfonífojì,
13 E os filisteus mais uma vez se espalharam ao longe no vale.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì tún béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dalóhùn pé, “Má ṣe gòkè tààrà, ṣùgbọ́n ẹ yí wọn ká, kí ẹ sì mú wọn níwájú igi muliberi.
14 Portanto, Davi voltou a consultar a Deus; e disse-lhe Deus: Não subas atrás deles; desvia-te, e vem sobre eles defronte às amoreiras.
15 Tí ó bá sì ṣe, tí ẹ̀yin bá ti gbọ́ ìró ẹsẹ̀ ní orí òkè igi muliberi, ẹ jáde fún ogun, nítorí èyí yóò fihàn pé Ọlọ́run ti jáde níwájú rẹ láti kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini.”
15 E será que, quando ouvires o som de um mover sobre a copa das amoreiras, sairás para a batalha; porque Deus saiu adiante para ferir o exército dos filisteus.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ṣe ohun tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini láti gbogbo ọ̀nà Gibeoni lọ sí Geseri.
16 Davi, portanto, fez como Deus lhe ordenou; e eles feriram o exército dos filisteus, desde Gibeão até Gezer.
17 Bẹ́ẹ̀ ni òkìkí Dafidi tàn ká gbogbo ilẹ̀ káàkiri, Olúwa sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè bẹ̀rù rẹ̀.
17 E a fama de Davi espalhou-se por todas as terras; e o ­SENHOR trouxe o temor a ele sobre todas as nações.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Crônicas 14, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.