1 Crônicas 11

Biblica® ní oore ọ̀fẹ́ láti lo Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YOR) vs BKJ

Sair da comparação
1 Gbogbo àwọn Israẹli kó ara wọn jọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ Dafidi ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa í ṣe.
1 Então, todo o Israel se reuniu com Davi em Hebrom, dizendo: Eis que somos teus ossos e tua carne.
2 Ní àtijọ́, kódà nígbà tí Saulu jẹ ọba, ìwọ ni ẹni tí ó darí Israẹli ní ojú ogun wọn. Olúwa Ọlọ́run rẹ sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò sì jẹ́ olùṣọ́ Israẹli ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún wọn.’ ”
2 E, além disso, em tempos passados, quando Saul foi rei sobre nós, tu eras aquele que fazias Israel sair e entrar; e o SENHOR teu Deus te disse: Tu pastorearás o meu povo Israel e tu serás soberano sobre Israel.
3 Nígbà tí gbogbo àwọn ìjòyè Israẹli tí wọ́n ti wá sọ́dọ̀ ọba Dafidi ni Hebroni. Ó sì ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn ní Hebroni níwájú Olúwa, wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba lórí Israẹli, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa láti ọwọ́ Samuẹli.
3 Portanto, vieram todos os anciãos de Israel até o rei em Hebrom; e o rei Davi fez um pacto com eles em Hebrom diante do SENHOR; e eles ungiram Davi rei sobre Israel, de acordo com a palavra do SENHOR por Samuel.
4 Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jáde lọ sí Jerusalẹmu (tí ṣe Jebusi). Àwọn Jebusi ara ilẹ̀ náà ń gbé níbẹ̀.
4 E Davi e todo o Israel foram até Jerusalém, a qual é Jebus; onde estavam os jebuseus, os habitantes da terra.
5 Àwọn ará ìlú Jebusi sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò sì gbọdọ̀ wọ ìhín yìí wá.” Ṣùgbọ́n Dafidi kó ìlú odi Sioni—èyí tí í ṣe ìlú Dafidi.
5 E os habitantes de Jebus disseram a Davi: Tu não virás para cá. Todavia, Davi tomou a fortaleza de Sião, que é a cidade de Davi.
6 Dafidi ti wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá tètè kọlu àwọn ará Jebusi ni yóò di olórí àti balógun.” Joabu ọmọ Seruiah sì kọ́kọ́ gòkè lọ, bẹ́ẹ̀ ni ó sì gba olórí.
6 E Davi disse: Qualquer que primeiro ferir os jebuseus será chefe e capitão. Assim, Joabe, o filho de Zeruia, subiu primeiro, e foi chefe.
7 Dafidi sì ń gbé inú ìlú odi, nítorí náà ni wọ́n fi ń pè é ni ìlú Dafidi.
7 E Davi habitou na fortaleza; é por isso que a chamaram de cidade de Davi.
8 Ó sì kọ́ àwọn ìlú náà yíkákiri; láti Millo yíkákiri; Joabu sì tún ìyókù àwọn ìlú náà ṣe.
8 E ele edificou a cidade ao redor, a saber, desde Milo até seus arredores; e Joabe restaurou o restante da cidade.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ń ga, ó sì pọ̀ sí i, nítorí pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà pẹ̀lú rẹ̀.
9 Assim, Davi se tornou cada vez maior; porque o SENHOR dos Exércitos estava com ele.
10 Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè alágbára ọkùnrin Dafidi, àwọn pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fún ìjọba rẹ̀ ní àtìlẹ́yìn tó lágbára láti mú un tàn káàkiri gbogbo ilẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣèlérí.
10 Estes também são os chefes dos homens valentes que Davi tinha, que se fortaleceram com ele no seu reino, e com todo o Israel, para fazê-lo rei, segundo a palavra do SENHOR acerca de Israel.
11 Èyí sì ni iye àwọn akọni ọkùnrin Dafidi:
11 E este é o número dos homens valentes que Davi tinha: Jasobeão, um hacmonita, o chefe dos capitães; ele ergueu a sua lança contra trezentos, de uma só vez os matou.
12 Lẹ́yìn rẹ̀ sì ni Eleasari ọmọ Dodo àwọn ará Ahohi, ọ̀kan lára àwọn mẹ́ta ọkùnrin alágbára.
12 E, depois dele estava Eleazar, o filho de Dodô, o aoíta, que era um dos três homens valentes.
13 Ó sì wà pẹ̀lú Dafidi ní Pasi-Dammimu nígbà tí àwọn ará Filistini kó ara wọn jọ láti jagun, níbi tí ilẹ̀ kan wà tí ó kún fún ọkà barle. Àwọn ènìyàn sì sálọ kúrò níwájú Filistini.
13 Ele estava com Davi em Pas-Damim, e ali os filisteus estavam reunidos para a batalha, onde havia uma parte do campo cheio de cevada; e o povo fugiu de diante dos filisteus.
14 Ṣùgbọ́n wọ́n mú ìdúró wọn ní àárín pápá náà. Wọ́n sì gbà a wọ́n sì gún àwọn ará Filistini mọ́lẹ̀, Olúwa sì mú ìgbàlà ńlá fún wọn.
14 E eles se puseram no meio daquela parte, e o livraram, e mataram os filisteus; e o SENHOR os salvou com um grande livramento.
15 Mẹ́ta nínú àwọn ọgbọ̀n ìjòyè sọ̀kalẹ̀ tọ́ Dafidi wá lọ sí orí àpáta nínú ihò Adullamu, nígbà tí àwọn ẹgbẹ́ Filistini sì dúró ní àfonífojì ní orí òkè Refaimu.
15 Ora, três dos trinta capitães desceram até a rocha, a Davi, na caverna de Adulão; e o exército dos filisteus acampou no vale dos Refains.
16 Ní àsìkò náà Dafidi sì ń bẹ nínú ìlú odi, ẹgbẹ́ ogun àwọn ará Filistini sì ń bẹ ní Bẹtilẹhẹmu.
16 E Davi estava, então, no forte, e a guarnição dos filisteus estava, então, em Belém.
17 Dafidi sí pòǹgbẹ fún omi ó sì wí pé, “Háà, ẹnìkan yóò ha bu omi láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu fún un mu?”
17 E Davi desejou, e disse: Ah, se alguém me desse de beber das águas do poço de Belém, que fica junto ao portão!
18 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mẹ́ta náà sì là láti ogun ará Filistini, ó sì fa omi jáde láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu ó sì gbé padà tọ Dafidi wá. Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti mu ú: dípò, ó sì tú jáde níwájú Olúwa.
18 E os três irromperam pelo exército dos filisteus, e retiraram água do poço de Belém, que ficava junto ao portão, e a tomaram e a trouxeram até Davi; porém Davi não quis beber dela, mas derramou-a para o SENHOR,
19 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí èmi ó má ṣe ṣe èyí!” ó wí pé. “Ṣé kí èmi kí ó mú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yí ẹni tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu?” Nítorí wọ́n fi ẹ̀mí wọn wéwu láti mú padà wá, Dafidi kò ní mu ú.
19 e disse: O meu Deus me proíba de fazer esta coisa; beberei eu o sangue destes homens que colocaram as suas vidas em risco? Porque com o risco das suas vidas eles a trouxeram; por isso ele não quis beber dela. Estas coisas fizeram estes três poderosos.
20 Abiṣai arákùnrin Joabu ìjòyè àwọn mẹ́ta. Ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún (300) àwọn ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn mẹ́ta.
20 E Abisai, o irmão de Joabe, foi o chefe dos três; por erguer a sua lança contra trezentos, ele os matou, e teve nome entre os três.
21 Ó sì gba ìlọ́po ọlá lórí àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ó sì di olórí wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ka kún ara wọn.
21 Dos três, ele foi mais ilustre do que os dois; porque ele foi o capitão deles; todavia não alcançou os três primeiros.
22 Benaiah ọmọ Jehoiada ó sì jẹ́ akọni oníjà láti Kabṣeeli, ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ agbára ńlá. Ó sì pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu, ó sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí inú ihò lákokò yìnyín dídì, ó sì pa kìnnìún kan
22 E Benaia, o filho de Joiada, o filho de um homem valente de Cabzeel, que havia feito muitos atos; ele matou dois homens de Moabe semelhantes a leões; também desceu e matou um leão em uma cova, em um dia com neve.
23 Ó sì pa ara Ejibiti ẹni tí ó ga ní ìwọ̀n ẹsẹ̀ méje àti ààbọ̀ ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti wọn ní ọ̀kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdábùú igi ahunṣọ àti ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, Benaiah sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú kùmọ̀. Ó sì gba ọ̀kọ̀ náà láti ọwọ́ ará Ejibiti ó sì pa á pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀.
23 E ele matou um egípcio, um homem de grande estatura, com cinco côvados de altura; e na mão do egípcio estava uma lança semelhante a um eixo de tecelão; e desceu até ele com uma vara, e arrancou a lança da mão do egípcio, e o matou com a sua própria lança.
24 Nǹkan wọ̀nyí sì ní ìwà akin Benaiah ọmọ Jehoiada; ohun náà pẹ̀lú sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn akọni ọkùnrin mẹ́ta.
24 Estas coisas fez Benaia, o filho de Joiada, e teve nome entre os três homens valentes.
25 Ó sì ní ọlá púpọ̀ ju àwọn ọgbọ̀n lọ, ṣùgbọ́n a kò kà á láàrín àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. Dafidi sì fi sí ìkáwọ́ àwọn ẹ̀ṣọ́.
25 Eis que ele foi ilustre entre os trinta, mas todavia não alcançou os três primeiros; e Davi o pôs sobre a sua guarda.
26 Àwọn akọni ọkùnrin náà nìyí:
26 Além disso, os homens valentes dos exércitos foram: Asael, o irmão de Joabe; Elanã, o filho de Dodô, de Belém;
27 Ṣamotu ará Harori,
27 Samote, o harodita; Heles, o pelonita;
28 Ira ọmọ Ikẹsi láti Tekoa,
28 Ira, o filho de Iques, o tecoíta; Abiezer, o anatotita;
29 Sibekai ará Huṣati,
29 Sibecai, o husatita; Ilai, o aoíta;
30 Maharai ará Netofa,
30 Maarai, o netofatita; Helede, o filho de Baaná, o netofatita;
31 Itai ọmọ Ribai láti Gibeah ní Benjamini,
31 Itai, o filho de Ribai, de Gibeá; que pertencia aos filhos de Benjamim, Benaia, o piratonita;
32 Hurai láti àfonífojì Gaaṣi,
32 Hurai, dos ribeiros de Gaás; Abiel, o arbatita;
33 Asmafeti ará Bahurimu
33 Azmavete, o baarumita; Eliaba, o saalbonita;
34 Àwọn ọmọ Haṣemu ará Gisoni
34 os filhos de Hasém, o gizonita: Jônatas, o filho de Sage, o hararita;
35 Ahiamu ọmọ Sakari ará Harari,
35 Aião, o filho de Sacar, o hararita; Elifal, o filho de Ur;
36 Heferi ará Mekerati,
36 Héfer, o mequeratita; Aías, o pelonita;
37 Hesro ará Karmeli
37 Hezro, o carmelita, Naarai, filho de Ezbai;
38 Joẹli arákùnrin Natani
38 Joel, o irmão de Natã; Mibar, o filho de Hagri;
39 Seleki ará Ammoni,
39 Zeleque, o amonita; Naarai, o berotita, o escudeiro de Joabe, o filho de Zeruia;
40 Ira ará Itri,
40 Ira, o itrita; Garebe, o itrita;
41 Uriah ará Hiti
41 Urias, o heteu; Zabade, o filho de Alai,
42 Adina ọmọ Ṣisa ará Reubeni, ẹni tí ó jẹ́ ìjòyè ará Reubeni, àti pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀.
42 Adina, o filho de Siza, o rubenita, um capitão dos rubenitas; e com ele trinta,
43 Hanani ọmọ Maaka.
43 Hanã, o filho de Maaca; e Josafá, o mitenita;
44 Ussia ará Asiterati,
44 Uzias, o astaratita; Sama e Jeiel, os filhos de Hotão, o aroerita;
45 Jediaeli ọmọ Ṣimri,
45 Jediael, o filho de Sinri; e Joá, seu irmão, o tizita,
46 Elieli ará Mahafi
46 Eliel, o maavita; e Jeribai, e Josavias, os filhos de Elnaão; e Itma, o moabita;
47 Elieli, Obedi àti Jaasieli ará Mesoba.
47 Eliel, o Obede, e Jaasiel, o mesobaíta.

Ler em outra tradução

Comparar com outra

Estude este capítulo no WhatsApp

Peça à IA da Bíblia Fala para explicar 1 Crônicas 11, comparar traduções ou montar um estudo — tudo direto pelo WhatsApp.